Saamu 4
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi.
4 Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́,
ìwọ Ọlọ́run òdodo mi,
Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi;
ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú?
Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?
3 Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, Olúwa ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀;
Olúwa yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.
4 (A)Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀;
Nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín,
ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.
5 Ẹ rú ẹbọ òdodo
kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, “Ta ni yóò ṣe rere fún wa?”
Olúwa, Jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,
7 Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi
ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.
8 Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà,
nítorí ìwọ nìkan, Olúwa, ni o
mú mi gbé láìléwu.
Psaumes 4
Segond 21
La sécurité qu’accorde l’Eternel
4 Au chef de chœur, avec instruments à cordes. Psaume de David.
2 Quand je crie, réponds-moi, Dieu de ma justice!
Quand j’étais dans la détresse, tu m’as mis au large.
Aie pitié de moi, écoute ma prière!
3 Vous les hommes, jusqu’à quand mépriserez-vous ma gloire?
Jusqu’à quand aimerez-vous ce qui est sans valeur
et rechercherez-vous le mensonge? – Pause.
4 Sachez que l’Eternel s’est choisi un homme fidèle.
L’Eternel entend quand je crie à lui.
5 *Si vous vous mettez en colère, ne péchez pas![a]
Parlez dans votre cœur, sur votre lit, et faites silence. – Pause.
6 Offrez des sacrifices conformes à la justice
et confiez-vous en l’Eternel.
7 Beaucoup disent: «Qui nous fera voir le bonheur?»
Fais briller la lumière de ton visage sur nous, Eternel!
8 Tu mets dans mon cœur plus de joie qu’ils n’en éprouvent
quand abondent leur blé, leur vin [et leur huile].
9 Je me couche et aussitôt je m’endors en paix,
car c’est toi seul, Eternel, qui me donnes la sécurité dans ma demeure.
Footnotes
- Psaumes 4:5 Si… péchez pas: cité en Ephésiens 4.26.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Version Segond 21 Copyright © 2007 Société Biblique de Genève by Société Biblique de Genève