Add parallel Print Page Options

Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀.

38 Olúwa, Má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin,
    ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ;
    kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀;
    wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.

Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́
    nítorí òmùgọ̀ mi.
Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi
    èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni
    kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi,
Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ;
    mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.

Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ;
    ìmí ẹ̀dùn mi kò sápamọ́ fún ọ.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀;
    bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi,
    àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi;
    àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun,
    wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.

13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;
    àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀,
    àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè;
    ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;
    nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”

17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú,
    ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi;
    àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀,
    ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi
    àwọn ni ọ̀tá mi
    nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.

21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa!
    Ọlọ́run mi, Má ṣe jìnnà sí mi.
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́,
    Olúwa, Olùgbàlà mi.

Do Not Forsake Me, O Lord

A Psalm of David, (A)for the memorial offering.

38 O Lord, (B)rebuke me not in your anger,
    nor discipline me in your wrath!
For your (C)arrows have sunk into me,
    and your hand (D)has come down on me.

There is (E)no soundness in my flesh
    because of your indignation;
there is no health in my (F)bones
    because of my sin.
For my (G)iniquities have gone over my head;
    like a heavy burden, they are too heavy for me.

My wounds stink and fester
    because of my foolishness,
I am (H)utterly bowed down and (I)prostrate;
    all the day I (J)go about mourning.
For my sides are filled with burning,
    and there is (K)no soundness in my flesh.
I am feeble and crushed;
    I (L)groan because of the tumult of my heart.

O Lord, all my longing is before you;
    my (M)sighing is not hidden from you.
10 My heart throbs; my strength fails me,
    and (N)the light of my eyes—it also has gone from me.
11 My (O)friends and companions (P)stand aloof from my (Q)plague,
    and my nearest kin (R)stand far off.

12 Those who seek my life (S)lay their snares;
    those who seek my hurt (T)speak of ruin
    and meditate (U)treachery all day long.

13 But I am like a deaf man; I do not hear,
    like (V)a mute man who does not open his mouth.
14 I have become like a man who does not hear,
    and in whose mouth are no (W)rebukes.

15 But for (X)you, O Lord, do I wait;
    it is you, O Lord my God, who will answer.
16 For I said, “Only (Y)let them not rejoice over me,
    who (Z)boast against me when my (AA)foot slips!”

17 For I am (AB)ready to fall,
    and my pain is ever before me.
18 I (AC)confess my iniquity;
    I am (AD)sorry for my sin.
19 But my foes are vigorous, they are mighty,
    and many are those who hate me (AE)wrongfully.
20 Those who (AF)render me evil for good
    (AG)accuse me because I (AH)follow after good.

21 Do not forsake me, O Lord!
    O my God, be not (AI)far from me!
22 (AJ)Make haste to help me,
    O Lord, my (AK)salvation!