Add parallel Print Page Options

Ti Dafidi.

25 Olúwa,
    ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.

Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ;
    Má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí
    Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
Ẹni tí ó dúró tì ọ́
    ojú kì yóò tì í,
àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí
    ni kí ojú kí ó tì.

Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa,
    kọ mi ní ipa tìrẹ;
ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi,
    Nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi;
    ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá,
    torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́
Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi
    tàbí ìrékọjá mi;
gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi
    nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.

Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa:
    nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára,
    ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin,
    fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa,
    dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.

12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa?
    Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà,
    àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀;
    ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa,
    nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.

16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi;
    nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi;
    kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi,
    kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi,
    tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.

20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀;
    Má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú,
    nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́;
    nítorí pé mo dúró tì ọ́.

22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run,
    nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!

A Plea for Deliverance and Forgiveness

A Psalm of David.

25 To (A)You, O Lord, I lift up my soul.
O my God, I (B)trust in You;
Let me not be ashamed;
(C)Let not my enemies triumph over me.
Indeed, let no one who [a]waits on You be ashamed;
Let those be ashamed who deal treacherously without cause.

(D)Show me Your ways, O Lord;
Teach me Your paths.
Lead me in Your truth and teach me,
For You are the God of my salvation;
On You I wait all the day.

Remember, O Lord, (E)Your tender mercies and Your lovingkindnesses,
For they are from of old.
Do not remember (F)the sins of my youth, nor my transgressions;
(G)According to Your mercy remember me,
For Your goodness’ sake, O Lord.

Good and upright is the Lord;
Therefore He teaches sinners in the way.
The humble He guides in justice,
And the humble He teaches His way.
10 All the paths of the Lord are mercy and truth,
To such as keep His covenant and His testimonies.
11 (H)For Your name’s sake, O Lord,
Pardon my iniquity, for it is great.

12 Who is the man that fears the Lord?
(I)Him shall [b]He teach in the way He chooses.
13 (J)He himself shall dwell in [c]prosperity,
And (K)his descendants shall inherit the earth.
14 (L)The secret of the Lord is with those who fear Him,
And He will show them His covenant.
15 (M)My eyes are ever toward the Lord,
For He shall [d]pluck my feet out of the net.

16 (N)Turn Yourself to me, and have mercy on me,
For I am [e]desolate and afflicted.
17 The troubles of my heart have enlarged;
Bring me out of my distresses!
18 (O)Look on my affliction and my pain,
And forgive all my sins.
19 Consider my enemies, for they are many;
And they hate me with [f]cruel hatred.
20 Keep my soul, and deliver me;
Let me not be ashamed, for I put my trust in You.
21 Let integrity and uprightness preserve me,
For I wait for You.

22 (P)Redeem Israel, O God,
Out of all their troubles!

Footnotes

  1. Psalm 25:3 Waits for You in faith
  2. Psalm 25:12 Or he
  3. Psalm 25:13 Lit. goodness
  4. Psalm 25:15 Lit. bring out
  5. Psalm 25:16 lonely
  6. Psalm 25:19 violent hatred