Add parallel Print Page Options

Saamu ti Dafidi

15 Olúwa, ta ni yóò máa ṣe àtìpó nínú àgọ́ rẹ?
    Ta ni yóò máa gbé ní òkè mímọ́ rẹ?

Ẹni tí ń rìn déédé
    tí ó sì ń sọ òtítọ́,
    láti inú ọkàn rẹ̀;
tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn,
    tí kò ṣe ibi sí aládùúgbò rẹ̀
    tí kò sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí ẹnìkejì rẹ̀,
ní ojú ẹni tí ènìyànkénìyàn di gígàn
    ṣùgbọ́n ó bọ̀wọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa,
Ẹni tí ó búra sí ibi ara rẹ̀
    àní tí kò sì yípadà,
tí ó ń yá ni lówó láìsí èlé
    tí kò sì gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lòdì sí aláìlẹ́ṣẹ̀.

Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe èyí
    ni a kì yóò mì láéláé.

Who Shall Dwell on Your Holy Hill?

A Psalm of David.

15 O Lord, (A)who shall sojourn in your (B)tent?
    Who shall dwell on your (C)holy hill?

He who (D)walks blamelessly and (E)does what is right
    and (F)speaks truth in his heart;
who (G)does not slander with his tongue
    and does no evil to his neighbor,
    nor (H)takes up a reproach against his friend;
(I)in whose eyes a vile person is despised,
    but who honors those who fear the Lord;
who (J)swears to his own hurt and does not change;
who (K)does not put out his money at interest
    and (L)does not take a bribe against the innocent.
He who does these things shall never be (M)moved.