Jakọbu 5
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìkìlọ̀ fún àwọn aninilára ọlọ́rọ̀
5 Ẹ wá nísinsin yìí, ẹ̀yin ọlọ́rọ̀, ẹ máa sọkún kí ẹ sì máa pohùnréré ẹkún nítorí òsì tí ó ń bọ̀ wá ta yín. 2 Ọrọ̀ yín díbàjẹ́, kòkòrò sì ti jẹ aṣọ yín. 3 Wúrà òun fàdákà yín díbàjẹ́; ìbàjẹ́ wọn ni yóò sì ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, tí yóò sì jẹ ẹran-ara yín bí iná. Ẹ̀yin tí kó ìṣúra jọ de ọjọ́ ìkẹyìn. 4 Kíyèsi i, ọ̀yà àwọn alágbàṣe tí wọ́n ti ṣe ìkórè oko yín, èyí tí ẹ kò san, ń ké rara; àti igbe àwọn tí ó ṣe ìkórè sì ti wọ inú etí Olúwa àwọn ọmọ-ogun. 5 Ẹ̀yin ti jẹ adùn ní ayé, ẹ̀yin sì ti fi ara yín fún ayé jíjẹ; ẹ̀yin ti mú ara yín sanra de ọjọ́ pípa. 6 Ẹ̀yin ti dá ẹ̀bi fún olódodo, ẹ sì ti pa á; ẹni tí kò kọ ojú ìjà sí yín.
Sùúrù nínú ìjìyà
7 Nítorí náà ará, ẹ mú sùúrù títí di ìpadà wá Olúwa. Kíyèsi i, àgbẹ̀ a máa retí èso iyebíye ti ilẹ̀, a sì mú sùúrù dè é, títí di ìgbà àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò. 8 Ẹ̀yin pẹ̀lú, ẹ mú sùúrù; ẹ fi ọkàn yín balẹ̀: nítorí ìpadà wá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀. 9 Ẹ má ṣe kùn sí ọmọnìkejì yín, ará, kí a má ba à dá a yín lẹ́bi: kíyèsi i, onídàájọ́ dúró ní ẹnu ìlẹ̀kùn.
10 Ará mi, ẹ fi àwọn wòlíì tí ó ti ń sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa ṣe àpẹẹrẹ ìyà jíjẹ, àti sùúrù. 11 (A)Sá à wò ó, àwa a máa ka àwọn tí ó fi ara dà ìyà sí ẹni ìbùkún. Ẹ̀yin ti gbọ́ ti sùúrù Jobu, ẹ̀yin sì rí ìgbẹ̀yìn tí Olúwa ṣe; pé Olúwa kún fún ìyọ́nú, ó sì ní àánú.
12 (B)Ṣùgbọ́n ju ohun gbogbo lọ, ará mi, ẹ má ṣe ìbúra, ìbá à ṣe fífi ọ̀run búra, tàbí ilẹ̀, tàbí ìbúra-kíbúra mìíràn. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí “Bẹ́ẹ̀ ni” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni; àti “Bẹ́ẹ̀ kọ́” yín jẹ́ bẹ́ẹ̀ kọ́; kí ẹ má ba à bọ́ sínú ẹ̀bi.
Àdúrà ìgbàgbọ́
13 Inú ẹnikẹ́ni ha bàjẹ́ nínú yín bí? Jẹ́ kí ó gbàdúrà. Inú ẹnikẹ́ni ha dùn? Jẹ́ kí ó kọrin mímọ́. 14 Ẹnikẹ́ni ha ṣe àìsàn nínú yín bí? Kí ó pe àwọn àgbà ìjọ, kí wọ́n sì gbàdúrà sórí rẹ̀, kí wọn fi òróró kùn ún ní orúkọ Olúwa: 15 Àdúrà ìgbàgbọ́ yóò sì gba aláìsàn náà là, Olúwa yóò sì gbé e dìde; bí ó bá sì ṣe pé ó ti dẹ́ṣẹ̀, a ó dáríjì í. 16 Ẹ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín fún ara yín, kí ẹ sì máa gbàdúrà fún ara yín, kí a lè mú yín láradá. Iṣẹ́ tí àdúrà olódodo ń ṣe ní agbára púpọ̀.
17 (C)Ènìyàn bí àwa ni Elijah, ó gbàdúrà gidigidi pé kí òjò kí ó má ṣe rọ̀, òjò kò sì rọ̀ sórí ilẹ̀ fún ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà. 18 (D)Ó sì tún gbàdúrà, ọ̀run sì tún rọ̀jò, ilẹ̀ sì so èso rẹ̀ jáde.
19 Ará, bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ṣìnà kúrò nínú òtítọ́, tí ẹni kan sì yí i padà; 20 Jẹ́ kí ó mọ̀ pé, ẹni tí ó bá yí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan padà kúrò nínú ìṣìnà rẹ̀, yóò gba ọkàn kan là kúrò lọ́wọ́ ikú, yóò sì bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.
James 5
English Standard Version
Warning to the Rich
5 Come now, (A)you rich, weep and howl for the (B)miseries that are coming upon you. 2 (C)Your riches have rotted and (D)your garments are moth-eaten. 3 Your gold and silver have corroded, and their corrosion will be evidence against you and will eat your flesh like fire. (E)You have laid up treasure (F)in the last days. 4 Behold, (G)the wages of the laborers who mowed your fields, which you kept back by fraud, are crying out against you, and (H)the cries of the harvesters have reached the ears of (I)the Lord of hosts. 5 (J)You have lived on the earth in luxury and (K)in self-indulgence. You have fattened your hearts in (L)a day of slaughter. 6 You have condemned and (M)murdered (N)the righteous person. He does not resist you.
Patience in Suffering
7 Be patient, therefore, brothers,[a] until the coming of the Lord. See how the farmer waits for the precious fruit of the earth, being patient about it, until it receives (O)the early and the late rains. 8 You also, be patient. (P)Establish your hearts, for the coming of the Lord (Q)is at hand. 9 Do not grumble against one another, brothers, (R)so that you may not be judged; behold, (S)the Judge is standing (T)at the door. 10 As an example of suffering and patience, brothers, take (U)the prophets who spoke in the name of the Lord. 11 Behold, we consider those blessed who remained steadfast. You have heard of (V)the steadfastness of Job, and you have seen (W)the purpose of the Lord, how (X)the Lord is compassionate and merciful.
12 But above all, my brothers, (Y)do not swear, either by heaven or by earth or by any other oath, but let your “yes” be yes and your “no” be no, so that you may not fall under condemnation.
The Prayer of Faith
13 Is anyone among you suffering? Let him pray. Is anyone cheerful? Let him (Z)sing praise. 14 Is anyone among you sick? Let him call for the elders of the church, and let them pray over him, (AA)anointing him with oil in the name of the Lord. 15 And the prayer of faith will save the one who is sick, and the Lord will raise him up. And (AB)if he has committed sins, he will be forgiven. 16 Therefore, (AC)confess your sins to one another and pray for one another, (AD)that you may be healed. (AE)The prayer of a righteous person has great power as it is working.[b] 17 Elijah was a man (AF)with a nature like ours, and (AG)he prayed fervently that it might not rain, and for (AH)three years and six months it did not rain on the earth. 18 (AI)Then he prayed again, and heaven gave rain, and the earth bore its fruit.
19 My brothers, (AJ)if anyone among you wanders from the truth and someone (AK)brings him back, 20 let him know that whoever brings back a sinner from his wandering (AL)will save his soul from death and (AM)will cover a multitude of sins.
Footnotes
- James 5:7 Or brothers and sisters; also verses 9, 10, 12, 19
- James 5:16 Or The effective prayer of a righteous person has great power
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
The ESV® Bible (The Holy Bible, English Standard Version®), © 2001 by Crossway, a publishing ministry of Good News Publishers. ESV Text Edition: 2025.